29 pé ìwọ kì yóò ṣe wá ní ibi, bí àwa pẹ̀lú kò ti ṣe ọ́ ní aburú, tí a sì ń ṣe ọ́ dáradára, tí a sì rán ọ jáde ní àlàáfíà láì ṣe ọ́ ní ibi, kíyèsi Olúwa sì ti bùkún fún ọ.”
30 Ísáákì sì ṣe àsè fún wọn, wọn sì jẹ, wọ́n sì mu.
31 Ní òwúrọ̀ ọjọ́ kejì wọn búra fún ara wọn. Ísáákì sì rán wọn lọ, wọ́n sì lọ ní àlàáfíà.
32 Ní ọjọ́ náà gan-an ni àwọn ìránṣẹ́ Ísáákì wá sọ fún un pé àwọn ti kan omi ní kànga kan tí àwọn gbẹ́.
33 Ó sì pe orúkọ kànga náà ní Ṣébà (kànga májẹ̀mu), títí di òní olónìí, orúkọ ìlú náà ni Bíáṣébà.
34 Nígbà tí Ísọ̀ pé ọmọ ogójì ọdún (40) ó fẹ́ ọmọbìnrin kan tí a ń pè ní Júdíìtì, ọmọ Béérì, ará Hítì, ó sì tún fẹ́ Báṣémátì, ọmọ Élónì ará Hítì.
35 Fífẹ́ tí a fẹ́ àwọn obìnrin wọ̀nyí jẹ́ ìbànújẹ́ fún Ísáákì àti Rèbékà.