2 Inú sì bí Jákọ́bù sí i, ó sì wí pé, “Èmi ha wà ní ipò Olúwa, ẹni tí ó mú ọ yàgàn bí?”
3 Nígbà náà ni Rákélì wí pé, “Bílíhà ìránṣẹ́bìnrin mi nìyìí, bá a lòpọ̀, kí ó ba à le bí ọmọ fún mi, kí èmi si le è tipaṣẹ̀ rẹ̀ ní ọmọ.”
4 Báyìí ni Rákélì fi Bílíhà fún Jákọ́bù ní aya, ó sì bá a lò pọ̀.
5 Bílíhà sì lóyún, ó sì bí ọmọkùnrin kan fún Jákọ́bù.
6 Rákélì sì wí pé, “Ọlọ́run ti ṣe ìdájọ́ mi; ó sì ti gbọ́ ohún ẹ̀bẹ̀ mi, ó sì fún mi ni ọmọkùnrin kan.” Nítorí ìdí èyí ni ó ṣe pe orúkọ rẹ̀ ní Dánì.
7 Bílíhà, ọmọ ọ̀dọ̀ Rákélì sì tún lóyún, ó sì bí ọmọkùnrin kéjì fún Jákọ́bù.
8 Nígbà náà ni Rákélì wí pé, “Mo ti bá ẹ̀gbọ́n mi ja ìjàkadì ńlá, èmi sì ti borí.” Ó sì pe orúkọ rẹ̀ ní Náfítalì.