Jẹ́nẹ́sísì 38:17-23 BMY

17 Ó sì wí pé, “Èmi yóò fi ọmọ ewúrẹ́ kan ránṣẹ sí ọ láti inú agbo ẹran.”Obìnrin náà sì dáhùn pé, “Ṣé ìwọ yóò fún mi ní ohun kan gẹ́gẹ́ bí ẹ̀rí títí tí ìwọ yóò fi fi ránṣẹ́?”

18 Júdà sì bi í pé, “Ẹ̀rí wo ni kí n fún ọ?”Ó sì dáhùn pé, “Èdìdì ìdámọ̀ okùn àti ọ̀pá ìtìlẹ̀ rẹ ti ń bẹ ní ọwọ́ rẹ.” Ó sì kó wọn fún un, ó sì sùn tì í, obìnrin náà sì lóyún nípaṣẹ̀ rẹ̀.

19 Lẹ́yìn ìgbà tí ó lọ, ó bọ́ ìbòjú ojú rẹ̀, ó sì tún wọ aṣọ opó rẹ̀ padà.

20 Nígbà náà ni Júdà fi ọmọ ewúrẹ́ náà rán ọ̀rẹ́ rẹ̀ sí obìnrin náà, kí ó ba à lè rí àwọn nǹkan tí ó fi ṣe ìdúró gbà padà. Ṣùgbọ́n wọn kò bá obìnrin náà níbẹ̀.

21 Ó béèrè lọ́wọ́ àwọn ènìyàn àdúgbò náà pé, “Níbo ni aṣẹ́wó (aṣẹ́wó ibi ojúbọ òrìṣa) tí ó wà ní etí ọ̀nà Énáímù wà?”Wọ́n sì dá a lóhùn pé, “Kò sí aṣẹ́wó kankan níbí”

22 Ó sì padà lọ sọ́dọ̀ Júdà ó wí fún-un pé, “Èmí kò rí i, à ti pé àwọn aládùúgbò ibẹ̀ sọ pé kò sí aṣẹ́wó kankan níbẹ̀.”

23 Nígbà náà ni Júdà wí pé, “Jẹ́ kí ó máa kó àwọn ohun tí ó wà lọ́wọ́ rẹ̀ lọ bí kò ṣe bẹ́ẹ̀ a ó di ẹlẹ́yà. Mo sáà fi ọmọ ewúrẹ́ ránṣẹ́ sí i, ṣùgbọ́n ìwọ kò rí òun.”