Jẹ́nẹ́sísì 48:14-20 BMY

14 Ísírẹ́lì sì na ọwọ́ ọ̀tún rẹ̀ jáde, ó sì gbe lé Éfúráímù lórí, bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé òun ni àbúrò, ó sì fi ọwọ́ rẹ̀ tàṣé ara wọn, ó sì na ọwọ́ òsì lé Mánásè lórí, bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé Mánásè ni àkọ́bí.

15 Nígbà náà ni ó súre fún Jósẹ́fù wí pé,“Ǹjẹ́ kí Ọlọ́run, ẹni tí baba miÁbúráhámù àti Ísáákì rìn níwájú Rẹ̀,Ọlọ́run tí ó ti jẹ́ olùtọ́jú àti aláàbòmi ní gbogbo ọjọ́ ayé mi títí di òní,

16 Ańgẹ́lì tí ó ti gbà mí kúrò lọ́wọ́ gbogbo ewu,kí ó súre fún àwọn ọmọkùnrin wọ̀nyí.Kí a máa fi orúkọ́ mi pè wọ́n àti orúkọ àwọn baba miÁbúráhámù àti Ísáákì,kí wọn kí ó sì pọ̀ sí i lọ́pọ̀lọpọ̀lórí ilẹ̀ ayé.”

17 Nígbà tí Jósẹ́fù rí i pé baba òun gbé ọwọ́ ọ̀tún lé Éfúráímù lórí, inú rẹ̀ bàjẹ́, ó sì gbá ọwọ́ baba rẹ̀ mú láti gbé ọwọ́ rẹ̀ kúrò lórí Éfúráímù lọ sí orí Mánásè.

18 Jósẹ́fù wí fun pé, “Rárá, baba mi, èyí ni àkọ́bí, orí rẹ̀ ni kí ìwọ kí o gbé ọwọ́ ọ̀tún rẹ lé.”

19 Ṣùgbọ́n baba rẹ̀ kò gbà, ó wí pé, “Mo mọ̀, ọmọ mi, mo mọ̀. Òun náà yóò di orílẹ̀-èdè, òun náà yóò sì di ńlá. Ṣùgbọ́n àbúrò rẹ̀ yóò di ẹni ńlá jù ú lọ, irú ọmọ rẹ yóò sì di ọ̀pọ̀lọpọ̀ orílẹ̀-èdè.”

20 Ó súre fún wọn lọ́jọ́ náà pé,“Ní orúkọ yín ni Ísírẹ́lì yóò máa súre yìí pé:‘Kí Ọlọ́run ṣe ọ́ bí i ti Éfúráímù àti Mánásè.’ ”