Jẹ́nẹ́sísì 20:1-7 BMY

1 Ábúráhámù sì kó kúrò níbẹ̀ lọ sí ìhà gúsù ó sì ń gbé ní agbede-méjì Kádésì àti Ṣúrì; ó sì gbé ní ìlú Gérárì fún ìgbà díẹ̀.

2 Ábúráhámù sì sọ ní ti Ṣárà aya rẹ̀ níbẹ̀ pé, “Arábìnrin mi ni.” Ábímélékì ọba Gérárì sì ránṣẹ́ mú Ṣárà wá sí ààfin rẹ̀.

3 Ṣùgbọ́n Ọlọ́run tọ Ábímélékì wá ní ojú àlá lọ́jọ́ kan, ó sì wí fún un pé, “Kíyèsi, kò sí ohun tí o fi sàn ju òkú lọ, nítorí obìnrin tí ìwọ mú sọ́dọ̀, aya aláya ni.”

4 Ṣùgbọ́n Ábímélékì kò tí ì bá obìnrin náà lò pọ̀, nítorí náà ó wí pé, “Olúwa ìwọ yóò run orílẹ̀ èdè aláìlẹ́bi bí?

5 Ǹjẹ́ òun kò sọ fún mi pé, ‘Arábìnrin mi ni,’ obìnrin náà pẹ̀lú sì sọ pé, ‘arákùnrin mí ni’? Ní òtítọ́ pẹ̀lú ọ̀kàn mímọ́ àti ọwọ́ mímọ́, ni mo ṣe èyí.”

6 Nígbà náà ni Ọlọ́run wí fún un nínú àlá náà pé, “Bẹ́ẹ̀ ni, mo mọ̀ pé pẹ̀lú òtítọ́ inú ni ìwọ ṣe èyí, èyí ni mo fi pa ọ́ mọ́ tí ń kò jẹ́ kí o dẹ́ṣẹ̀ sí mi. Ìdí nìyí tí n kò fi jẹ́ kí o ní ìbálòpọ̀ pẹ̀lú obìnrin náà.

7 Níṣinyìí, dá aya ọkùnrin náà padà, nítorí pé wòlíì ni, yóò sì gbàdúrà fún ọ, ìwọ yóò sì yè. Ṣùgbọ́n bí ìwọ kò bá dá a padà, mọ̀ dájú pé ìwọ àti gbogbo ẹni tíí ṣe tìrẹ yóò kú.”