Jẹ́nẹ́sísì 20:4-10 BMY

4 Ṣùgbọ́n Ábímélékì kò tí ì bá obìnrin náà lò pọ̀, nítorí náà ó wí pé, “Olúwa ìwọ yóò run orílẹ̀ èdè aláìlẹ́bi bí?

5 Ǹjẹ́ òun kò sọ fún mi pé, ‘Arábìnrin mi ni,’ obìnrin náà pẹ̀lú sì sọ pé, ‘arákùnrin mí ni’? Ní òtítọ́ pẹ̀lú ọ̀kàn mímọ́ àti ọwọ́ mímọ́, ni mo ṣe èyí.”

6 Nígbà náà ni Ọlọ́run wí fún un nínú àlá náà pé, “Bẹ́ẹ̀ ni, mo mọ̀ pé pẹ̀lú òtítọ́ inú ni ìwọ ṣe èyí, èyí ni mo fi pa ọ́ mọ́ tí ń kò jẹ́ kí o dẹ́ṣẹ̀ sí mi. Ìdí nìyí tí n kò fi jẹ́ kí o ní ìbálòpọ̀ pẹ̀lú obìnrin náà.

7 Níṣinyìí, dá aya ọkùnrin náà padà, nítorí pé wòlíì ni, yóò sì gbàdúrà fún ọ, ìwọ yóò sì yè. Ṣùgbọ́n bí ìwọ kò bá dá a padà, mọ̀ dájú pé ìwọ àti gbogbo ẹni tíí ṣe tìrẹ yóò kú.”

8 Ní òwúrọ̀ kùtùkùtù ọjọ́ kejì, Ábímélékì pe gbogbo àwọn ìjòyè rẹ̀. Nígbà tí ó sì ṣọ gbogbo ohun tí ó sẹlẹ̀ fún wọn, ẹ̀rù bà wọ́n gidigidi.

9 Nígbà náà ni Ábímélékì pe Ábúráhámù ó sì wí fún un pé, “Èwo ni èyí tí ìwọ ṣe sí wa yìí? Ẹ̀sẹ̀ wo ni mo sẹ̀ ọ́ tí ìwọ fi mú ìdálẹ́bi ńlá wá sí orí èmi àti ìjọba mi? Kò yẹ kí ìwọ hu irú ìwà yìí sí mi.”

10 Ábímélékì sì bi Ábúráhámù pé, “Kín ló dé tí ìwọ fi ṣe èyí?”