Jẹ́nẹ́sísì 35:1-7 BMY

1 Nígbà náà ni Ọlọ́run wí fún Jákọ́bù pé, “Gòkè lọ sí Bẹ́tẹ́lì kí o sì tẹ̀dó ṣíbẹ̀, kí o mọ pẹpẹ níbẹ̀ fún Ọlọ́run tó farahàn ọ́ nígbà tí o ń sá lọ kúrò níwájú Íṣọ̀ arákùnrin rẹ.”

2 Nítorí náà, Jákọ́bù wí fún gbogbo ará ilé rẹ̀ pé, “Ẹ mú gbogbo àjòjì òrìsà tí ó wà lọ́dọ̀ yín kúrò, kí ẹ ya ara yín sí mímọ́, kí ẹ sì pààrọ̀ aṣọ yín.

3 Nígbà náà ni kí ẹ wá, kí ẹ jẹ́ kí a lọ sí Bẹ́tẹ́lì, níbi tí n ó ti mọ pẹpẹ fún Ọlọ́run, tí ó dá mi lóhùn ní ọjọ́ ìpọ́njú mi tí ó sì ti ń pẹ̀lú mi níbi gbogbo tí mo ń lọ.”

4 Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n fún Jákọ́bù ní gbogbo àjòjì òrìsà tí ó wà lọ́wọ́ wọn, àti yẹtí etí wọn, Jákọ́bù sì bo gbogbo wọn mọ́lẹ̀ sabẹ́ igi Óákù ní Ṣékémù.

5 Wọ́n sì bẹ̀rẹ̀ ìrìn-àjò wọn. Ìbẹ̀rù láti ọ̀dọ̀ Ọlọ́run sì ń bá lé gbogbo ìlú tí wọ́n ń là kọjá ní ọ̀nà wọn tó bẹ́ẹ̀ tí kò sí ẹni tí ó le è dojú ìjà kọ wọ́n.

6 Jákọ́bù àti gbogbo àwọn tí ó wà pẹ̀lú rẹ̀ sì dé sí Lúsì (Bẹ́tẹ́lì) tí ó wà ní ilẹ̀ Kénánì.

7 Níbẹ̀ ni ó sì mọ pẹpẹ kan tí ó pè ní El-Bẹ́tẹ́lì (Ọlọ́run Bẹ́tẹ́lì), nítorí níbẹ̀ ni Ọlọ́run ti gbé fi ara hàn-án nígbà tí ó ń sá lọ fún arákùnrin rẹ̀.