16 Nígbàkígbà tí òsùmàrè bá yọ ní ojú ọ̀run, èmi yóò rí i, èmi yóò sì rántí májẹ̀mú ayérayé tí ń bẹ láàrin Ọlọ́run àti gbogbo ẹ̀dá alààyè tí ń bẹ ní ayé.”
17 Ọlọ́run sì wí fún Nóà pé, “Èyí ni àmì májẹ̀mú tí mo ti fi ìdí rẹ̀ múlẹ̀ láàrin èmi àti gbogbo alààyè ní ayé.”
18 Àwọn ọmọ Nóà tí ó jáde nínú ọkọ̀ ni Ṣémù, Ámù àti Jáfétì. (Ámù ni bàba Kénánì).
19 Nípaṣẹ̀ àwọn ọmọ Nóà mẹ́tẹ̀ẹ̀ta yìí ni gbogbo ènìyàn ti tàn ká gbogbo ilẹ̀ ayé.
20 Nóà bẹ̀rẹ̀ iṣẹ́ àgbẹ̀, ó sì gbin ọgbà àjàrà.
21 Ó mu àmupara nínú ọtí wáìnì àjàrà rẹ̀, ó sì tú ara rẹ̀ sí ìhòòhò, ó sì sùn nínú àgọ́ rẹ̀.
22 Ámù tí í ṣe baba Kénání sì rí baba rẹ̀ ní ìhòòhò bẹ́ẹ̀ ni ó sì lọ sọ fún àwọn arákùnrin rẹ̀ méjèèjì ní ìta.