25 Ísáákì sì kọ́ pẹpẹ kan ṣíbẹ̀, ó sì pe orúkọ Olúwa. Níbẹ̀ ni ó pàgọ́ rẹ̀ sí, àwọn ìránṣẹ́ rẹ sì gbẹ́ kànga kan ṣíbẹ̀.
26 Nígbà náà ni Ábímélékì tọ̀ ọ́ wá láti Gérárì, àti Áhúsátì, olùdámọ̀ràn rẹ̀ àti Fíkólì, olórí ogun rẹ̀.
27 Ísáákì sì bi wọ́n léèrè pé, “Èéṣe tí ẹ̀yin tọ̀ mí wá, níwọ̀n ìgbà tí ẹ̀yin kórìra mi tí ẹ sì lé mi jáde kúrò lọ́dọ̀ yin?”
28 Wọ́n dáhùn pé, “A rí i dájú pé Olúwa wà pẹ̀lú rẹ, nítorí náà ni a fi rò ó wí pé, ó yẹ kí májẹ̀mú kí o wà láàrin àwa àti ìwọ. Jẹ́ kí a ṣe àdéhùn
29 pé ìwọ kì yóò ṣe wá ní ibi, bí àwa pẹ̀lú kò ti ṣe ọ́ ní aburú, tí a sì ń ṣe ọ́ dáradára, tí a sì rán ọ jáde ní àlàáfíà láì ṣe ọ́ ní ibi, kíyèsi Olúwa sì ti bùkún fún ọ.”
30 Ísáákì sì ṣe àsè fún wọn, wọn sì jẹ, wọ́n sì mu.
31 Ní òwúrọ̀ ọjọ́ kejì wọn búra fún ara wọn. Ísáákì sì rán wọn lọ, wọ́n sì lọ ní àlàáfíà.