20 Ọba ranṣẹ, nwọn si tú u silẹ; ani ijoye awọn enia, o si jọwọ rẹ̀ lọwọ lọ.
21 O fi jẹ oluwa ile rẹ̀, ati ijoye gbogbo ini rẹ̀.
22 Lati ma ṣe akoso awọn ọmọ-alade rẹ̀ nipa ifẹ rẹ̀; ati lati ma kọ́ awọn igbimọ rẹ̀ li ọgbọ́n.
23 Israeli si wá si Egipti pẹlu; Jakobu si ṣe atipo ni ilẹ Hamu.
24 O si mu awọn enia rẹ̀ bi si i pipọ̀-pipọ̀; o si mu wọn lagbara jù awọn ọta wọn lọ.
25 O yi wọn li aiya pada lati korira awọn enia rẹ̀, lati ṣe arekereke si awọn iranṣẹ rẹ̀.
26 O rán Mose iranṣẹ rẹ̀; ati Aaroni, ẹniti o ti yàn.