17 Lórí wọn ni àwọn ẹyẹ ń tẹ́ ìtẹ́wọn sí,àkọ̀ sì ń kọ́ ilé rẹ̀ sórí igi firi.
18 Òkè gíga ni ilé ewúrẹ́ igbó,abẹ́ àpáta sì ni ibùgbé ehoro.
19 O dá òṣùpá láti máa sàmì àkókò,oòrùn sì mọ àkókò wíwọ̀ rẹ̀.
20 O mú kí òkùnkùn ṣú, alẹ́ sì lẹ́,gbogbo ẹranko ìgbẹ́ sìń jẹ kiri.
21 Àwọn ẹgbọ̀rọ̀ kinniun ń bú fún ìjẹ,wọ́n ń wo ojú Ọlọrun fún oúnjẹ.
22 Nígbà tí oòrùn bá là, wọn á wọ́ lọ;wọn á lọ dùbúlẹ̀ sinu ihò wọn.
23 Ọmọ eniyan á sì jáde lọ síbi iṣẹ́ rẹ̀,á lọ síbi làálàá rẹ̀ títí di àṣáálẹ́.