Orin Dafidi 72 BM

Adura Ọba

1 Ọlọrun, gbé ìlànà òtítọ́ rẹ lé ọba lọ́wọ́;kọ́ ọmọ ọba ní ọ̀nà òdodo rẹ.

2 Kí ó lè máa fi òdodo ṣe ìdájọ́ àwọn eniyan rẹ,kí ó sì máa dá ẹjọ́ àwọn tí ìyà ń jẹ ní ọ̀nà ẹ̀tọ́;

3 kí àwọn eniyan tí ó gbé orí òkè ńlá lè rí alaafia,kí nǹkan sì dára fún àwọn tí ń gbé orí òkè kéékèèké.

4 Jẹ́ kí ó máa gbèjà àwọn eniyan tí ìyà ń jẹ;kí ó máa gba àwọn ọmọ talaka sílẹ̀;kí ó sì rún àwọn aninilára wómúwómú.

5 Ọlọrun, jẹ́ kí àwọn eniyan rẹ máa bẹ̀rù rẹ láti ìran dé ìran,níwọ̀n ìgbà tí oòrùn bá ń ràn, tí òṣùpá sì ń yọ.

6 Jẹ́ kí ọba ó dàbí òjò tí ó rọ̀ sórí koríko tí a ti géàní, bí ọ̀wààrà òjò tí ń rin ilẹ̀.

7 Kí ìwà rere ó gbèrú ní ìgbà tirẹ̀;kí alaafia ó gbilẹ̀ títítí òṣùpá kò fi ní yọ mọ́.

8 Kí ìjọba rẹ̀ ó lọ láti òkun dé òkun,ati láti odò ńlá títí dé òpin ayé.

9 Àwọn tí ń gbé aṣálẹ̀ yóo máa foríbalẹ̀ fún un;àwọn ọ̀tá rẹ̀ yóo sì máa fi ẹnu gbo ilẹ̀ níwájú rẹ̀.

10 Àwọn ọba Taṣiṣi ati àwọn ọba erékùṣù gbogboyóo máa san ìṣákọ́lẹ̀ fún un;àwọn ọba Ṣeba ati ti Seba yóo máa mú ẹ̀bùn wá.

11 Gbogbo àwọn ọba yóo máa wólẹ̀ fún un;gbogbo àwọn orílẹ̀-èdè yóo sì máa sìn ín.

12 Nítorí pé a máa gba talaka tí ó bá ké pè é sílẹ̀;a sì máa gba àwọn tí ìyà ń jẹ sílẹ̀,ati àwọn tí kò ní olùrànlọ́wọ́.

13 A máa ṣíjú àánú wo àwọn aláìní ati talaka,a sì máa gba àwọn talaka sílẹ̀.

14 A máa gbà wọ́n lọ́wọ́ àwọn aninilára ati oníwà ipá,ẹ̀mí wọn sì ṣe iyebíye ní ojú rẹ̀.

15 Ẹ̀mí rẹ̀ yóo gùn,a óo máa fi wúrà Ṣeba ta á lọ́rẹ,a óo máa gbadura fún un nígbà gbogbo;a óo sì máa súre fún un tọ̀sán-tòru.

16 Ọkà yóo pọ̀ lóko,yóo máa mì lẹ̀gbẹ̀ lórí òkè;èso rẹ̀ yóo dàbí ti Lẹbanoni,eniyan yóo pọ̀ ní ìlú,bíi koríko ninu pápá.

17 Orúkọ ọba óo wà títí lae,òkìkí rẹ̀ óo sì máa kàn níwọ̀n ìgbà tí oòrùn bá ń ràn;àwọn eniyan óo máa fi orúkọ rẹ̀ súre fún ara wọn,gbogbo orílẹ̀-èdè óo sì máa pè é ní olóríire.

18 Ẹni-ìyìn ni OLUWA Ọlọrun Israẹli,ẹni tí ó ń ṣe iṣẹ́ ìyanu tí ẹlòmíràn kò lè ṣe.

19 Ẹni ìyìn títí lae ni ẹni tí orúkọ rẹ̀ lókìkí,kí òkìkí rẹ̀ gba ayé kan!Amin! Amin.