Orin Dafidi 65 BM

Ìyìn ati Ọpẹ́

1 Ọlọrun, ìwọ ni ìyìn yẹ ní Sioni,ìwọ ni a óo san ẹ̀jẹ́ wa fún,

2 ìwọ tí ń gbọ́ adura!Ọ̀dọ̀ rẹ ni gbogbo eniyan ń bọ̀,

3 nítorí ẹ̀ṣẹ̀ wọn.Nígbà tí ẹ̀ṣẹ̀ wa bá borí wa,ìwọ a máa dáríjì wá.

4 Ayọ̀ ń bẹ fún ẹni tí o yàn,tí o mú wá sí ọ̀dọ̀ rẹ,láti máa gbé inú àgbàlá rẹ.Àwọn ire inú ilé rẹ yóo tẹ́ wa lọ́rùn,àní, àwọn ire inú tẹmpili mímọ́ rẹ!

5 Iṣẹ́ òdodo tí ó bani lẹ́rù ni o fi dá wa lóhùn,Ọlọrun olùgbàlà wa.Ìwọ ni gbogbo àwọn tí ó wà lórí ilẹ̀ ayé gbẹ́kẹ̀lé,ati àwọn tí wọn wà lórí omi òkun ní ọ̀nà jíjìn réré.

6 Ìwọ tí o fi agbára fi ìdí àwọn òkè ńlá múlẹ̀;tí o sì fi agbára di ara rẹ ní àmùrè.

7 O mú híhó òkun dákẹ́ jẹ́ẹ́,ariwo ìgbì wọn rọlẹ̀ wọ̀ọ̀;o sì paná ọ̀tẹ̀ àwọn eniyan.

8 Àwọn tí ń gbé ìpẹ̀kun ayé sì ń bẹ̀rùnítorí àwọn iṣẹ́ ìyanu rẹ;o mú kí àwọn eniyan, láti ìlà oòrùn títí dé ìwọ̀ rẹ̀, hó ìhó ayọ̀.

9 Ò ń ṣìkẹ́ ayé, o sì ń bomi rin ín,o mú kí ilẹ̀ jí kí ó sì lẹ́tù lójú;o mú kí omi kún inú odò ìwọ Ọlọrun,o mú kí ọkà hù lórí ilẹ̀;nítorí pé bẹ́ẹ̀ ni o ṣe ṣètò rẹ̀.

10 O bomi rin poro oko rẹ̀ lọpọlọpọ,o ṣètò àwọn ẹsẹ̀ rẹ̀;o rọ òjò tó mú kí ilẹ̀ rọ̀,o sì mú kí ohun ọ̀gbìn rẹ̀ dàgbà.

11 O mú kí ìkórè oko pọ̀ yanturu ní òpin ọdún;gbogbo ipa ọ̀nà rẹ sì kún fún ọpọlọpọ ìkórè oko.

12 Gbogbo pápá oko kún fún ẹran ọ̀sìn,àwọn ẹ̀gbẹ́ òkè sì kún fún ohun ayọ̀,

13 ẹran ọ̀sìn bo pápá oko bí aṣọ,ọkà bo gbogbo àfonífojì, ó sì so jìngbìnnì,wọ́n ń hó, wọ́n sì ń kọrin ayọ̀.