Orin Dafidi 86 BM

Adura Ìrànlọ́wọ́

1 Tẹ́tí sí mi OLUWA, kí o sì gbọ́ adura mi,nítorí òtòṣì ati aláìní ni mí.

2 Dá ẹ̀mí mi sí nítorí olùfọkànsìn ni mí;gba èmi iranṣẹ rẹ tí ó gbẹ́kẹ̀lé ọ là;ìwọ ni Ọlọrun mi.

3 Ṣàánú mi, OLUWA,nítorí ìwọ ni mò ń kígbe pè tọ̀sán-tòru.

4 Mú inú iranṣẹ rẹ dùn,nítorí ìwọ ni mò ń gbadura sí.

5 Nítorí pé olóore ni ọ́, OLUWA,o máa ń dárí jini;ìfẹ́ rẹ tí kì í yẹ̀ sì pọ̀ sí gbogbo àwọn tí ń ké pè ọ́.

6 Fetí sí adura mi, OLUWA,gbọ́ igbe ẹ̀bẹ̀ mi.

7 Ní ọjọ́ ìpọ́njú mo ké pè ọ́,nítorí pé o máa ń gbọ́ adura mi.

8 OLUWA, kò sí èyí tí ó dàbí rẹ ninu àwọn oriṣa;kò sì sí iṣẹ́ ẹni tí ó dàbí iṣẹ́ rẹ.

9 Gbogbo àwọn orílẹ̀-èdè tí o dá ni yóo wá,OLUWA, wọn óo máa forí balẹ̀ níwájú rẹ:wọn óo sì máa yin orúkọ rẹ lógo.

10 Nítorí pé o tóbi, o sì ń ṣe ohun ìyanu;ìwọ nìkan ni Ọlọrun.

11 OLUWA, kọ́ mi ní ọ̀nà rẹ,kí n lè máa rìn ninu òtítọ́ rẹ;kí n lè pa ọkàn pọ̀ láti máa bẹ̀rù orúkọ rẹ.

12 Gbogbo ọkàn ni mo fi dúpẹ́ lọ́wọ́ rẹ, OLUWA, Ọlọrun mi;n óo máa yin orúkọ rẹ lógo títí lae.

13 Nítorí ìfẹ́ rẹ tí kì í yẹ̀ tóbi sí mi;o ti yọ ọkàn mi kúrò ninu isà òkú.

14 Ọlọrun, àwọn agbéraga dìde sí mi;ẹgbẹ́ àwọn ìkà, aláìláàánú kan ń lépa ẹ̀mí mi;wọn kò sì bìkítà fún ọ.

15 Ṣugbọn ìwọ, OLUWA, ni Ọlọrun aláàánú ati olóore;o kì í tètè bínú, o sì kún fún ìfẹ́ tí kì í yẹ̀, ati òtítọ́.

16 Kọjú sí mi, kí o sì ṣàánú mi;fún èmi iranṣẹ rẹ ní agbára rẹ;kí o sì gba èmi ọmọ iranṣẹbinrin rẹ là.

17 Fi àmì ojurere rẹ hàn mí,kí àwọn tí ó kórìíra mi lè rí i,kí ojú sì tì wọ́n;nítorí pé ìwọ, OLUWA, ni o ràn mí lọ́wọ́,tí o sì tù mí ninu.