26 Ibẹ̀ ni ọkọ̀ ojú omi ń gbà lọ,ati Lefiatani tí o dá láti máa ṣeré ninu òkun.
27 Ojú rẹ ni gbogbo wọn ń wò,fún ìpèsè oúnjẹ ní àkókò.
28 Nígbà tí o bá fún wọn, wọn á kó o jọ,nígbà tí o bá la ọwọ́,wọn á jẹ ohun dáradára ní àjẹyó.
29 Bí o bá fojú pamọ́,ẹ̀rù á bà wọ́n,bí o bá gba ẹ̀mí wọn, wọn á kú,wọn á sì pada di erùpẹ̀.
30 Nígbà tí o rán ẹ̀mí rẹ jáde,wọ́n di ẹ̀dá alààyè,o sì sọ orí ilẹ̀ di ọ̀tun.
31 Kí ògo OLUWA máa wà títí lae,kí OLUWA máa yọ̀ ninu iṣẹ́ rẹ̀.
32 Ẹni tí ó wo ilẹ̀, tí ilẹ̀ mì tìtì,tí ó fọwọ́ kan òkè, tí wọ́n bẹ̀rẹ̀ sí yọ èéfín.