4 Ìwọ tí o fi ẹ̀fúùfù ṣe iranṣẹ,tí o sì fi iná ati ahọ́n iná ṣe òjíṣẹ́ rẹ.
5 Ìwọ tí o gbé ayé kalẹ̀ lórí ìpìlẹ̀ rẹ̀,tí kò sì le yẹ̀ laelae.
6 O fi ibú omi bò ó bí aṣọ,omi sì borí àwọn òkè ńlá.
7 Nígbà tí o bá wọn wí, wọ́n sá,nígbà tí o sán ààrá, wọ́n sá sẹ́yìn.
8 Wọ́n ṣàn kọjá lórí òkèlọ sí inú àfonífojì,sí ibi tí o yàn fún wọn.
9 O ti pa ààlà tí wọn kò gbọdọ̀ kọjá,kí wọn má baà tún bo ayé mọ́lẹ̀ mọ́.
10 Ìwọ ni o mú kí àwọn orísun máa tú omi jáde ní àfonífojì;omi wọn sì ń ṣàn láàrin àwọn òkè.