7 Nígbà tí o bá wọn wí, wọ́n sá,nígbà tí o sán ààrá, wọ́n sá sẹ́yìn.
8 Wọ́n ṣàn kọjá lórí òkèlọ sí inú àfonífojì,sí ibi tí o yàn fún wọn.
9 O ti pa ààlà tí wọn kò gbọdọ̀ kọjá,kí wọn má baà tún bo ayé mọ́lẹ̀ mọ́.
10 Ìwọ ni o mú kí àwọn orísun máa tú omi jáde ní àfonífojì;omi wọn sì ń ṣàn láàrin àwọn òkè.
11 Ninu omi wọn ni gbogbo ẹranko tí ń mu,ibẹ̀ sì ni àwọn kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ igbó tí ń rẹ òùngbẹ.
12 Lẹ́bàá orísun wọnyini àwọn ẹyẹ ń gbé,wọ́n sì ń kọrin lórí igi.
13 Láti ibùgbé rẹ lókè ni o tí ń bomi rin àwọn òkè ńlá.Ilẹ̀ sì mu àmutẹ́rùn nípa iṣẹ́ ọwọ́ rẹ.