41 Ó la àpáta, omi tú jáde,ó sì ṣàn ninu aṣálẹ̀ bí odò.
42 Nítorí pé ó ranti ìlérí mímọ́ rẹ̀,ati Abrahamu, iranṣẹ rẹ̀.
43 Ó fi ayọ̀ kó àwọn eniyan rẹ̀ jáde,ó kó àwọn àyànfẹ́ rẹ̀ jáde pẹlu orin.
44 Ó fún wọn ní ilẹ̀ àwọn orílẹ̀-èdè mìíràn,wọ́n sì jogún èrè iṣẹ́ àwọn eniyan náà.
45 Kí wọ́n lè máa mú àṣẹ rẹ̀ ṣẹ,kí wọ́n sì máa pa òfin rẹ̀ mọ́.Ẹ yin OLUWA!