13 Kò pẹ́ tí wọ́n tún fi gbàgbé iṣẹ́ rẹ̀,wọn kò sì dúró gba ìmọ̀ràn rẹ̀.
14 Wọ́n ṣe ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ ní aṣálẹ̀,wọ́n sì dán Ọlọrun wò.
15 Ó fún wọn ní ohun tí wọ́n bèèrè,ṣugbọn ó fi àìsàn ajẹnirun ṣe wọ́n.
16 Nígbà tí wọ́n ṣe ìlara sí Mose ninu ibùdó,ati sí Aaroni, ẹni mímọ́ OLÚWA.
17 Ilẹ̀ yanu, ó gbé Datani mì,ó sì bo Abiramu ati àwọn tí ó tẹ̀lé e mọ́lẹ̀.
18 Iná sọ láàrin wọn,ó sì jó àwọn eniyan burúkú náà run.
19 Wọ́n yá ère ẹgbọ̀rọ̀ mààlúù ní Horebu,wọ́n sì bọ ère tí wọ́n dà.