18 Oúnjẹ rùn sí wọn,wọ́n sì súnmọ́ bèbè ikú.
19 Nígbà náà ni wọ́n ké pe OLUWA ninu ìpọ́njú wọn,ó sì yọ wọ́n ninu ìṣẹ́ wọn.
20 Ó sọ̀rọ̀, ó sì mú wọn lára dá,ó tún kó wọn yọ ninu ìparun.
21 Jẹ́ kí wọn máa yin OLUWA nítorí ìfẹ́ rẹ̀ tí kì í yẹ̀,àní, nítorí àwọn iṣẹ́ ìyanu tí ó ṣe fún eniyan.
22 Kí wọn máa rú ẹbọ ọpẹ́,kí wọn sì máa fi orin ayọ̀ ròyìn iṣẹ́ rẹ̀.
23 Àwọn kan wọ ọkọ̀ ojú omi,wọ́n ń ṣòwò lórí agbami òkun,
24 wọ́n rí ìṣe OLUWA,àní iṣẹ́ ìyanu rẹ̀ ninu ibú.