4 Nítorí pé ìfẹ́ rẹ tí kì í yẹ̀ tóbi, ó ga ju ọ̀run lọ,òtítọ́ rẹ sì kan ojú ọ̀run.
5 Kí á gbé ọ ga ju ọ̀run lọ, Ọlọrun,kí ògo rẹ sì kárí gbogbo ayé.
6 Kí á lè gba àyànfẹ́ rẹ là,fi ọwọ́ agbára rẹ gbà wá, kí o sì dá mi lóhùn.
7 Ọlọrun ti sọ̀rọ̀ ninu ilé mímọ́ rẹ̀,ó ní, “Tayọ̀tayọ̀ ni n óo fi pín Ṣekemu,n óo sì pín àfonífojì Sukotu.
8 Tèmi ni Gileadi, tèmi sì ni Manase.Efuraimu ni àkẹtẹ̀ àṣíborí mi,Juda sì ni ọ̀pá àṣẹ mi.
9 Moabu ni ìkòkò ìwẹsẹ̀ mi,lórí Edomu ni n óo bọ́ bàtà mi lé,n óo sì hó ìhó ìṣẹ́gun lórí Filistia.”
10 Ta ni yóo mú mi wọ inú ìlú olódi náà?Ta ni yóo mú mi lọ sí Edomu?