5 Kí á gbé ọ ga ju ọ̀run lọ, Ọlọrun,kí ògo rẹ sì kárí gbogbo ayé.
6 Kí á lè gba àyànfẹ́ rẹ là,fi ọwọ́ agbára rẹ gbà wá, kí o sì dá mi lóhùn.
7 Ọlọrun ti sọ̀rọ̀ ninu ilé mímọ́ rẹ̀,ó ní, “Tayọ̀tayọ̀ ni n óo fi pín Ṣekemu,n óo sì pín àfonífojì Sukotu.
8 Tèmi ni Gileadi, tèmi sì ni Manase.Efuraimu ni àkẹtẹ̀ àṣíborí mi,Juda sì ni ọ̀pá àṣẹ mi.
9 Moabu ni ìkòkò ìwẹsẹ̀ mi,lórí Edomu ni n óo bọ́ bàtà mi lé,n óo sì hó ìhó ìṣẹ́gun lórí Filistia.”
10 Ta ni yóo mú mi wọ inú ìlú olódi náà?Ta ni yóo mú mi lọ sí Edomu?
11 Ọlọrun, o kò ha ti kọ̀ wá sílẹ̀?Ọlọrun, o ò bá àwọn ọmọ ogun wa lọ sójú ogun mọ́.