14 Kí OLUWA máa ranti ẹ̀ṣẹ̀ àwọn baba rẹ̀,kí ó má sì pa ẹ̀ṣẹ̀ ìyá rẹ̀ rẹ́.
15 Kí OLUWA máa ranti ẹ̀ṣẹ̀ wọn nígbà gbogbo,kí á má sì ranti ìran wọn mọ́ láyé.
16 Nítorí pé kò ronú láti ṣàánú,ṣugbọn ó ṣe inúnibíni talaka ati aláìní,ati sí oníròbìnújẹ́ títí a fi pa wọ́n.
17 Ó fẹ́ràn láti máa ṣépè;nítorí náà kí èpè rẹ̀ dà lé e lórí;inú rẹ̀ kò dùn sí ìre,nítorí náà kí ìre jìnnà sí i.
18 Ó gbé èpè wọ̀ bí ẹ̀wù,kí èpè mù ún bí omi,kí ó sì wọ inú egungun rẹ̀ dé mùdùnmúdùn.
19 Kí èpè di aṣọ ìbora fún un,ati ọ̀já ìgbànú.
20 Bẹ́ẹ̀ ni kí OLUWA ṣe sí àwọn ọ̀tá mi,àwọn tí ń sọ̀rọ̀ ibi nípa mi!