8 Ṣe é ní ẹlẹ́mìí kúkúrú,kí ohun ìní rẹ̀ di ti àwọn alọ́nilọ́wọ́gbà.
9 Kí àwọn ọmọ rẹ̀ di aláìníbaba,kí aya rẹ̀ di opó.
10 Kí àwọn ọmọ rẹ̀ di alárìnká,kí wọn máa ṣagbe kiri;kí á lé wọn jáde kúrò ninu ahoro tí wọn ń gbé.
11 Kí ẹni tí ó jẹ lówó gba gbogbo ohun ìní rẹ̀,kí ẹni ẹlẹ́ni sì kó èrè iṣẹ́ rẹ̀.
12 Kí ó má bá aláàánú pàdé,kí ẹnikẹ́ni má sì ṣàánú àwọn ọmọ rẹ̀ tí wọ́n ti di aláìníbaba.
13 Kí ìran rẹ̀ run,kí orúkọ rẹ̀ parẹ́ lórí àwọn ọmọ rẹ̀.
14 Kí OLUWA máa ranti ẹ̀ṣẹ̀ àwọn baba rẹ̀,kí ó má sì pa ẹ̀ṣẹ̀ ìyá rẹ̀ rẹ́.