21 O bá àwọn onigbeeraga wí, àwọn ẹni ègún,tí wọn kò pa òfin rẹ mọ́.
22 Mú ẹ̀gàn ati àbùkù wọn kúrò lára mi,nítorí pé mo ti pa òfin rẹ mọ́.
23 Bí àwọn ìjòyè tilẹ̀ gbìmọ̀ràn ọ̀tẹ̀ nítorí mi,sibẹ, èmi iranṣẹ rẹ yóo ṣe àṣàrò lórí ìlànà rẹ.
24 Àwọn òfin rẹ ni dídùn inú mi,àwọn ni olùdámọ̀ràn mi.
25 Mo di ẹni ilẹ̀,sọ mí di alààyè gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ rẹ.
26 Nígbà tí mo jẹ́wọ́ gbogbo ìṣe mi, o dá mi lóhùn;kọ́ mi ní ìlànà rẹ.
27 La òfin rẹ yé mi,n óo sì máa ṣe àṣàrò lórí iṣẹ́ ìyanu rẹ.