10 Ẹni tí ó pa àwọn àkọ́bí ní ilẹ̀ Ijipti,nítorí pé ìfẹ́ rẹ̀ tí kì í yẹ̀ wà títí lae;
11 ó sì kó àwọn ọmọ Israẹli jáde kúrò láàrin wọn,nítorí pé ìfẹ́ rẹ̀ tí kì í yẹ̀ wà títí lae.
12 Pẹlu ipá ati ọwọ́ líle ni ó fi kó wọn jáde,nítorí pé ìfẹ́ rẹ̀ tí kì í yẹ̀ wà títí lae.
13 Ẹni tí ó pín Òkun Pupa sí meji,nítorí pé ìfẹ́ rẹ̀ tí kì í yẹ̀ wà títí lae;
14 ó sì mú àwọn ọmọ Israẹli kọjá láàrin rẹ̀,nítorí pé ìfẹ́ rẹ̀ tí kì í yẹ̀ wà títí lae;
15 ṣugbọn ó bi Farao ati àwọn ọmọ ogunrẹ̀ ṣubú ninu Òkun Pupa,nítorí pé ìfẹ́ rẹ̀ tí kì í yẹ̀ wà títí lae.
16 Ẹni tí ó mú àwọn eniyan rẹ̀ la aṣálẹ̀ já,nítorí pé ìfẹ́ rẹ̀ tí kì í yẹ̀ wà títí lae;