5 Ẹni tí ó fi ọgbọ́n dá ọ̀run,nítorí pé ìfẹ́ rẹ̀ tí kì í yẹ̀ wà títí lae;
6 ẹni tí ó tẹ́ ilẹ̀ lé orí omi,nítorí pé ìfẹ́ rẹ̀ tí kì í yẹ̀ wà títí lae;
7 ẹni tí ó dá àwọn ìmọ́lẹ̀ ńlá,nítorí pé ìfẹ́ rẹ̀ tí kì í yẹ̀ wà títí lae.
8 Ó dá oòrùn láti máa ṣe àkóso ọ̀sán,nítorí pé ìfẹ́ rẹ̀ tí kì í yẹ̀ wà títí lae.
9 Ó dá òṣùpá ati ìràwọ̀ láti máa ṣe àkóso òru,nítorí pé ìfẹ́ rẹ̀ tí kì í yẹ̀ wà títí lae.
10 Ẹni tí ó pa àwọn àkọ́bí ní ilẹ̀ Ijipti,nítorí pé ìfẹ́ rẹ̀ tí kì í yẹ̀ wà títí lae;
11 ó sì kó àwọn ọmọ Israẹli jáde kúrò láàrin wọn,nítorí pé ìfẹ́ rẹ̀ tí kì í yẹ̀ wà títí lae.