5 OLUWA, fa ojú ọ̀run wá sílẹ̀, kí o sì sọ̀kalẹ̀ wá,fọwọ́ kan àwọn òkè ńlá, kí wọ́n máa rú èéfín.
6 Jẹ́ kí mànàmáná kọ, kí o sì tú wọn ká,ta ọfà rẹ, kí o tú wọn ká.
7 Na ọwọ́ rẹ sílẹ̀ láti òkè,kí o yọ mí ninu ibú omi;kí o sì gbà mí lọ́wọ́ àwọn àjèjì,
8 tí ẹnu wọn kún fún irọ́,tí ọwọ́ ọ̀tún wọn sì kún fún èké.
9 Ọlọrun, n óo kọ orin titun sí ọ,n óo fi hapu olókùn mẹ́wàá kọrin sí ọ.
10 Ìwọ ni ò ń fún àwọn ọba ní ìṣẹ́gun,tí o sì gba Dafidi, iranṣẹ rẹ, là.
11 Gbà mí lọ́wọ́ idà ìkà,gbà mí lọ́wọ́ àwọn àjèjì,tí ẹnu wọ́n kún fún irọ́,tí ọwọ́ ọ̀tún wọn sì kún fún èké.