2 OLUWA ní ń kọ́ ìlú Jerusalẹmu;òun ni yóo kó àwọn ọmọ Israẹli tí a fọ́n ká jọ.
3 Ó ń tu àwọn tí ọkàn wọn bàjẹ́ ninu,ó sì ń dí ọgbẹ́ wọn.
4 Òun ló mọ iye àwọn ìràwọ̀,òun ló sì fún gbogbo wọn lórúkọ.
5 OLUWA wa tóbi, ó sì lágbára pupọòye rẹ̀ kò ní ìwọ̀n.
6 OLUWA ní ń gbé àwọn onírẹ̀lẹ̀ ró,òun ni ó sì ń sọ àwọn eniyan burúkú di ilẹ̀ẹ́lẹ̀.
7 Ẹ kọ orin ọpẹ́ sí OLUWA,ẹ fi hapu kọ orin dídùn sí Ọlọrun wa.
8 Ẹni tí ó fi ìkùukùu bo ojú ọ̀run,ó pèsè òjò fún ilẹ̀,ó mú koríko hù lórí òkè.