9 Òun ni ó ń fún àwọn ẹranko ní oúnjẹ,tí ó sì ń bọ́ ọmọ ẹyẹ ìwò, tí ó ń ké.
10 Kì í ṣe agbára ẹṣin ni inú rẹ̀ dùn sí,kì í sì í ṣe inú agbára eniyan ni ayọ̀ rẹ̀ wà.
11 Ṣugbọn inú OLUWA dùn sí àwọn tí ó bẹ̀rù rẹ̀,àwọn tí ó ní ìrètí ninu ìfẹ́ rẹ̀ tí kì í yẹ̀.
12 Gbé OLUWA ga, ìwọ Jerusalẹmu!Yin Ọlọrun rẹ, ìwọ Sioni!
13 Ó fún ẹnubodè rẹ ní agbára,ó sì bukun àwọn tí ń gbé inú rẹ.
14 Ó jẹ́ kí alaafia wà ní ààlà ilẹ̀ rẹ,ó sì fi oúnjẹ tí ó dára bọ́ ọ lábọ̀ọ́yó.
15 Ó pàṣẹ lórí ilẹ̀ ayé,àṣẹ rẹ̀ sì múlẹ̀ kíá.