3 Mo ké pe OLUWA, ẹni tí ìyìn yẹ,ó sì gbà mí lọ́wọ́ àwọn ọ̀tá mi.
4 Ikú wé mọ́ mi bí okùn,ìparun sì bò mí mọ́lẹ̀ bíi rírú omi.
5 Isà òkú yí mi ká,tàkúté ikú sì dojú kọ mí.
6 Ninu ìpọ́njú mi mo ké pe OLUWA,Ọlọrun mi ni mo ké pè.Ó gbọ́ ohùn mi láti inú ilé mímọ́ rẹ̀,ó sì tẹ́tí sí igbe mi.
7 Ilẹ̀ ayé wárìrì, ó sì mì tìtì,ìpìlẹ̀ àwọn òkè mì jìgìjìgì;wọ́n wárìrì nítorí tí ó bínú.
8 Èéfín ṣẹ́ jáde láti ihò imú rẹ̀,iná ajónirun yọ jáde láti ẹnu rẹ̀;ẹ̀yinná sì ń jò bùlà láti ọ̀dọ̀ rẹ̀ wá.
9 Ó dẹ ojú ọ̀run sílẹ̀, ó sì sọ̀kalẹ̀ wá,ìkùukùu tó ṣókùnkùn biribiri sì wà lábẹ́ ẹsẹ̀ rẹ̀.