5 Tọ́ mi sí ọ̀nà òtítọ́ rẹ, sì máa kọ́ mi,nítorí ìwọ ni Ọlọrun olùgbàlà mi;ìwọ ni mo gbẹ́kẹ̀lé ní ọjọ́ gbogbo.
6 OLUWA, ranti àánú rẹ, ati ìfẹ́ rẹ tí kì í yẹ̀,nítorí wọ́n ti wà ọjọ́ ti pẹ́.
7 Má ranti ẹ̀ṣẹ̀ tí mo ti ṣẹ̀ ní ìgbà èwe mi,tabi ibi tí mo ti kọjá ààyè mi;ranti mi, OLUWA, nítorí ìfẹ́ rẹ tí kì í yẹ̀,ati nítorí oore rẹ.
8 Olóore ati olódodo ni OLÚWA,nítorí náà ni ó ṣe ń fi ọ̀nà han àwọn ẹlẹ́ṣẹ̀.
9 A máa tọ́ àwọn onírẹ̀lẹ̀ láti ṣe ohun tí ó tọ́,a sì máa kọ́ wọn ní ìlànà rẹ̀.
10 Gbogbo ọ̀nà OLUWA ni ó kún fún ìfẹ́ tí kì í yẹ̀ ati òtítọ́,fún àwọn tí ń pa majẹmu ati òfin rẹ̀ mọ́.
11 Nítorí orúkọ rẹ, OLUWA, dárí ẹ̀ṣẹ̀ mi jì mí,nítorí mo jẹ̀bi lọpọlọpọ.