14 Ṣugbọn, mo gbẹ́kẹ̀lé ọ, OLUWA,Mo ní, “Ìwọ ni Ọlọrun mi.”
15 Ìgbà mi ń bẹ ní ọwọ́ rẹ;gbà mí lọ́wọ́ àwọn ọ̀tá mi,ati lọ́wọ́ àwọn tí ń lépa mi.
16 Jẹ́ kí èmi iranṣẹ rẹ rí ojurere rẹ,gbà mí là, nítorí ìfẹ́ rẹ tí kì í yẹ̀.
17 Má jẹ́ kí ojú tì mí, OLUWA,nítorí ìwọ ni mò ń ké pè.Jẹ́ kí ojú ti àwọn eniyan burúkú;jẹ́ kí ẹnu wọn wọ wòwò títí wọ ibojì.
18 Jẹ́ kí àwọn òpùrọ́ yadi,àní àwọn tí ń fi ìgbéraga ati ẹ̀gàn sọ̀rọ̀ àìdára nípa olódodo.
19 Háà! Ohun rere mà pọ̀ lọ́wọ́ rẹ otí o ti sọ lọ́jọ̀ fún àwọn tí ó bẹ̀rù rẹ,tí o sì ti pèsè ní ìṣojú àwọn ọmọ eniyan,fún àwọn tí ó sá di ọ́.
20 O fi ìyẹ́ apá rẹ ṣíji bò wọ́n;o pa wọ́n mọ́ kúrò ninu rìkíṣí àwọn eniyan;o sì pa wọ́n mọ́ lábẹ́ ààbò rẹ,kúrò lọ́wọ́ ẹnu àwọn ẹlẹ́jọ́ wẹ́wẹ́.