20 Nítorí pé wọn kì í sọ̀rọ̀ alaafia sí àwọn tí wọn ń lọ jẹ́ẹ́jẹ́ wọnàfi kí wọ́n máa pète oríṣìíríṣìí ẹ̀tàn.
21 Wọ́n la ẹnu, wọ́n ń pariwo lé mi lórí,wọ́n ń wí pé, “Ìn hín ìn, a rí ọ, ojú wa ló ṣe!”
22 O ti rí i, OLUWA, má dákẹ́.OLUWA, má jìnnà sí mi.
23 Paradà, OLUWA, jí gìrì sí ọ̀ràn mi,gbèjà mi, Ọlọrun mi, ati OLUWA mi!
24 Dá mi láre, OLUWA, Ọlọrun mi, gẹ́gẹ́ bí òdodo rẹ;má sì jẹ́ kí wọ́n yọ̀ mí!
25 Má jẹ́ kí wọ́n wí láàrin ara wọn pé,“Ìn hín ìn, ọwọ́ wa ba ohun tí a fẹ́!”Má jẹ́ kí wọn wí pé,“A rẹ́yìn ọ̀tá wa.”
26 Jẹ́ kí ojú ti gbogbo àwọn tí ń yọ̀ pé ìpọ́njú dé bá mi;kí ìdààmú bá wọn;bá mi da aṣọ ìtìjú ati ẹ̀tẹ́ bo àwọn tí ń gbé àgbéré sí mi.