4 Jẹ́ kí ojú ó ti àwọn tí ń lépa ẹ̀mí mi,kí wọn ó tẹ́!Jẹ́ kí àwọn tí ń gbìmọ̀ ibi sí mi dààmú,kí wọ́n sì sá pada sẹ́yìn!
5 Kí wọ́n dàbí fùlùfúlù ninu afẹ́fẹ́,kí angẹli OLUWA máa lé wọn lọ!
6 Jẹ́ kí ojú ọ̀nà wọn ṣóòkùn, kí ó sì máa yọ̀,kí angẹli OLUWA máa lépa wọn!
7 Nítorí wọ́n dẹ àwọ̀n sílẹ̀ fún mi láìnídìí,wọ́n sì gbẹ́ kòtò sílẹ̀ dè mí láìnídìí.
8 Jẹ́ kí ìparun dé bá wọn lójijì,jẹ́ kí àwọ̀n tí wọ́n dẹ sílẹ̀ dè mí mú wọn;jẹ́ kí wọ́n kó sinu rẹ̀, kí wọ́n sì parun!
9 Nígbà náà ni n óo máa yọ̀ ninu OLUWA,n óo sì yọ ayọ̀ ńlá nítorí ìgbàlà rẹ̀.
10 N óo fi gbogbo ara wí pé,“OLUWA, ta ni ó dàbí rẹ?Ìwọ ni ò ń gba aláìlágbáralọ́wọ́ ẹni tí ó lágbáratí o sì ń gba aláìlágbára ati aláìnílọ́wọ́ ẹni tí ó fẹ́ fi wọ́n ṣe ìjẹ.”