1 OLUWA tóbi, ó sì yẹ kí á máa yìn ín lọpọlọpọní ìlú Ọlọrun wa.
2 Òkè mímọ́ rẹ̀, tí ó ga, tí ó sì lẹ́wà,ni ayọ̀ gbogbo ayé.Òkè Sioni, ní àríwá, lọ́nà jíjìn réré,ìlú ọba ńlá.
3 Ninu ilé ìṣọ́ ìlú náà, Ọlọrun ti fi ara rẹ̀ hàn bí ibi ìsádi.
4 Wò ó! Àwọn ọba kó ara wọn jọ;wọ́n jùmọ̀ gbógun tì í.
5 Nígbà tí wọ́n fojú kàn án, ẹnu yà wọ́n,ìpayà mú wọn, wọ́n sì sá;
6 ìwárìrì mú wọn níbẹ̀;ìrora sì bá wọn bí obinrin tí ń rọbí.