10 Ọlọrun, ìyìn rẹ tàn ká,bí orúkọ rẹ ṣe tàn dé òpin ayé,iṣẹ́ rere kún ọwọ́ rẹ.
11 Jẹ́ kí inú òkè Sioni kí ó dùn,kí gbogbo Juda sì máa yọ̀nítorí ìdájọ́ rẹ.
12 Ẹ rìn yí Sioni po; ẹ yí i ká;ẹ ka àwọn ilé ìṣọ́ rẹ̀;
13 ẹ ṣàkíyèsí odi rẹ̀;ẹ wọ inú gbogbo ilé ìṣọ́ rẹ̀ lọ,kí ẹ lè ròyìn fún ìran tí ń bọ̀
14 pe: “Ọlọrun yìí ni Ọlọrun wa,lae ati laelae.Òun ni yóo máa ṣe amọ̀nà wa títí lae.”