3 Ninu ilé ìṣọ́ ìlú náà, Ọlọrun ti fi ara rẹ̀ hàn bí ibi ìsádi.
4 Wò ó! Àwọn ọba kó ara wọn jọ;wọ́n jùmọ̀ gbógun tì í.
5 Nígbà tí wọ́n fojú kàn án, ẹnu yà wọ́n,ìpayà mú wọn, wọ́n sì sá;
6 ìwárìrì mú wọn níbẹ̀;ìrora sì bá wọn bí obinrin tí ń rọbí.
7 Ó fọ́ wọn bí afẹ́fẹ́ ìlà oòrùn tií fọ́ ọkọ̀ Taṣiṣi.
8 Bí a ti gbọ́, bẹ́ẹ̀ gan-an ni ó rí,ní ìlú OLUWA àwọn ọmọ ogun,ní ìlú Ọlọrun wa:Ọlọrun fi ìdí rẹ̀ múlẹ̀ títí lae.
9 Ninu tẹmpili rẹ, Ọlọrun,à ń ṣe àṣàrò lórí ìfẹ́ rẹ tí kì í yẹ̀.