5 Kí ló dé tí n óo fi bẹ̀rù ní àkókò ìyọnu,nígbà tí iṣẹ́ ibi àwọn tí ń ṣe inúnibíni mi bá yí mi ká,
6 àwọn tí wọ́n gbẹ́kẹ̀lé ọrọ̀ wọn,tí wọ́n sì ń yangàn nítorí wọ́n ní ọrọ̀ pupọ?
7 Dájúdájú, kò sí ẹni tí ó le ra ara rẹ̀ pada,tabi tí ó lè san owó ìràpadà ẹ̀mí rẹ̀ fún Ọlọrun;
8 nítorí pé ẹ̀mí eniyan níye lórí pupọ.Kò sí iye tí eniyan ní tí ó le kájú rẹ̀,
9 tí eniyan lè máa fi wà láàyè títí lae,kí ó má fojú ba ikú.
10 Yóo rí i pé ikú a máa pa ọlọ́gbọ́n,òmùgọ̀ ati òpè a sì máa rọ̀run;wọn a sì fi ọrọ̀ wọn sílẹ̀ fún ẹlòmíràn.
11 Ibojì wọn ni ilé wọn títí lae,ibẹ̀ ni ibùgbé wọn títí ayérayé,wọn ìbáà tilẹ̀ ní ilẹ̀ ti ara wọn.