5 Ẹ̀rù ati ìwárìrì dà bò mí,ìpayà sì bò mí mọ́lẹ̀.
6 Mo ní, “Èmi ìbá ní ìyẹ́ bí àdàbà!Ǹ bá fò lọ, ǹ bá lọ sinmi.
7 Áà! Ǹ bá lọ jìnnà réré,kí n lọ máa gbé inú ijù;
8 ǹ bá yára lọ wá ibi ààbòkúrò lọ́wọ́ afẹ́fẹ́ líle ati ìjì.”
9 Da èrò wọn rú, OLUWA,kí o sì dà wọ́n lédè rú;nítorí ìwà ipá ati asọ̀ pọ̀ ninu ìlú.
10 Tọ̀sán-tòru ni wọ́n ń yí orí odi rẹ̀ ká;ìwà ìkà ati ìyọnu ni ó sì pọ̀ ninu rẹ̀.
11 Ìparun wà ninu rẹ̀;ìnilára ati ìwà èrú kò sì kúrò láàrin ìgboro rẹ̀.