24 A ti rí ọ, Ọlọrun, bí o tí ń yan lọ,pẹlu ọ̀wọ́ èrò tí ń tẹ̀lé ọ lẹ́yìn.Ẹ wo Ọlọrun mi, ọba mi,bí ó ti ń yan wọ ibi mímọ́ rẹ̀,
25 àwọn akọrin níwájú,àwọn onílù lẹ́yìn,àwọn ọmọbinrin tí ń lu samba láàrin.
26 “Ẹ fi ọpẹ́ fún Ọlọrun ninu àwùjọ eniyan,ẹ̀yin ìran Israẹli, ẹ fi ọpẹ́ fún OLUWA.”
27 Ẹ wo Bẹnjamini tí ó kéré jù níwájú,ẹ wo ogunlọ́gọ̀ àwọn ìjòyè Juda,ẹ wo àwọn ìjòyè Sebuluni ati ti Nafutali.
28 Fi agbára rẹ hàn, Ọlọrun,fi agbára tí o ti fi jà fún wa hàn.
29 Nítorí Tẹmpili rẹ tí ó wà ní Jerusalẹmu,àwọn ọba yóo gbé ẹ̀bùn wá fún ọ.
30 Bá àwọn ẹranko ẹ̀dá tí ń gbé inú èèsún ní Ijipti wí;àwọn akọ mààlúù, láàrin agbo ẹran àwọn orílẹ̀-èdè.Tẹ àwọn tí ó fẹ́ràn owó mọ́lẹ̀;fọ́n àwọn orílẹ̀-èdè tí ó fẹ́ràn ogun ká.