17 Má ṣe fi ojú pamọ́ fún èmi, iranṣẹ rẹ,nítorí tí mo wà ninu ìdààmú,yára dá mi lóhùn.
18 Sún mọ́ mi, rà mí pada,kí o sì tú mi sílẹ̀ nítorí àwọn ọ̀tá mi!
19 O mọ ẹ̀gàn mi,o mọ ìtìjú ati àbùkù mi;o sì mọ gbogbo àwọn ọ̀tá mi.
20 Ẹ̀gàn ti mú kí inú mi bàjẹ́,tóbẹ́ẹ̀ tí ọkàn mi rẹ̀wẹ̀sìmò ń retí àánú ṣugbọn kò sí;mò ń retí olùtùnú, ṣugbọn n kò rí ẹnìkan.
21 Iwọ ni wọ́n sọ di oúnjẹ fún mi,nígbà tí òùngbẹ sì ń gbẹ mí,ọtí kíkan ni wọ́n fún mi mu.
22 Jẹ́ kí tabili oúnjẹ tí wọ́n tẹ́ fún arawọn di ẹ̀bìtì fún wọn;kí àsè ẹbọ wọn sì di tàkúté.
23 Jẹ́ kí ojú wọn ṣú,kí wọn má lè ríran;kí gbogbo ara wọn sì máa gbọ̀n rìrì.