20 Ẹ̀gàn ti mú kí inú mi bàjẹ́,tóbẹ́ẹ̀ tí ọkàn mi rẹ̀wẹ̀sìmò ń retí àánú ṣugbọn kò sí;mò ń retí olùtùnú, ṣugbọn n kò rí ẹnìkan.
21 Iwọ ni wọ́n sọ di oúnjẹ fún mi,nígbà tí òùngbẹ sì ń gbẹ mí,ọtí kíkan ni wọ́n fún mi mu.
22 Jẹ́ kí tabili oúnjẹ tí wọ́n tẹ́ fún arawọn di ẹ̀bìtì fún wọn;kí àsè ẹbọ wọn sì di tàkúté.
23 Jẹ́ kí ojú wọn ṣú,kí wọn má lè ríran;kí gbogbo ara wọn sì máa gbọ̀n rìrì.
24 Rọ òjò ibinu rẹ lé wọn lórí,kí o sì jẹ́ kí wọ́n rí gbígbóná ibinu rẹ.
25 Kí ibùdó wọn ó di ahoro,kí ẹnikẹ́ni má sì gbé inú àgọ́ wọn.
26 Nítorí ẹni tí o ti kọlù ni wọ́n tún gbógun tì;ẹni tí o ti ṣá lọ́gbẹ́ ni wọ́n sì tún ń pọ́n lójú.