18 Dájúdájú, OLUWA, tìrẹ ni ààbò wa;ìwọ, Ẹni Mímọ́ Israẹli ni ọba wa.
19 Ní ìgbàanì, o sọ ninu ìran fún olùfọkànsìn rẹ pé,“Mo ti fi adé dé alágbára kan lórí,mo ti gbé ẹnìkan ga tí a yàn láàrin àwọn eniyan.
20 Mo ti rí Dafidi, iranṣẹ mi;mo ti fi òróró mímọ́ mi yàn án;
21 kí ọwọ́ agbára mi lè máa gbé e ró títí lae,kí ọwọ́ mi sì máa fún un ní okun.
22 Ọ̀tá kan kò ní lè borí rẹ̀,bẹ́ẹ̀ ni àwọn eniyan burúkú kò ní tẹ orí rẹ̀ ba.
23 N óo run ọ̀tá rẹ̀ níwájú rẹ̀;n óo sì bá àwọn tí ó kórìíra rẹ̀ kanlẹ̀.
24 Òtítọ́ mi ati ìfẹ́ mi tí kì í yẹ̀ yóo wà pẹlu rẹ̀;orúkọ mi ni yóo sì máa fi ṣẹgun.