12 Wọ́n óo fi ọwọ́ wọn gbé ọ sókè,kí o má baà fi ẹsẹ̀ gbún òkúta.
13 O óo rìn kọjá lórí kinniun ati paramọ́lẹ̀;ẹgbọ̀rọ̀ kinniun ati ejò ńlá ni o óo fi ẹsẹ̀ tẹ̀ mọ́lẹ̀.
14 OLUWA ní, “Nítorí pé ó nífẹ̀ẹ́ sí mi,n óo gbà á là;n óo dáàbò bò ó, nítorí pé ó mọ orúkọ mi.
15 Yóo pè mí, n óo sì dá a lóhùn;n óo wà pẹlu rẹ̀ ninu ìṣòro,n óo yọ ọ́ ninu rẹ̀, n óo dá a lọ́lá.
16 N óo fi ẹ̀mí gígùn tẹ́ ẹ lọ́rùn,n óo sì gbà á là.”