2 yóo wí fún OLUWA pé,“Ìwọ ni ààbò ati odi mi,Ọlọrun mi, ẹni tí mo gbẹ́kẹ̀lé.”
3 Nítorí yóo yọ ọ́ ninu okùn àwọn pẹyẹpẹyẹati ninu àjàkálẹ̀ àrùn apanirun.
4 Yóo da ìyẹ́ rẹ̀ bò ọ́,lábẹ́ ìyẹ́ apá rẹ̀ ni o óo ti rí ààbò;òtítọ́ rẹ̀ ni yóo jẹ́ asà ati apata rẹ.
5 O ò ní bẹ̀rù ìdágìrì òru,tabi ọfà tí ń fò kiri ní ọ̀sán,
6 tabi àjàkálẹ̀ àrùn tí ń jà kiri ninu òkùnkùn,tabi ìparun tí ń ṣeni lófò ní ọ̀sán gangan.
7 Ẹgbẹrun lè ṣubú ní ẹ̀gbẹ́ rẹ,tabi ẹgbaarun ni apá ọ̀tún rẹ;ṣugbọn kò ní súnmọ́ ọ̀dọ̀ rẹ.
8 Ojú nìkan ni óo kàn máa fi rí wọn,tí o óo sì máa fi wo èrè àwọn eniyan burúkú.