4 Nítorí ìwọ, OLUWA, ti mú inú mi dùn nípa iṣẹ́ rẹ;OLUWA, mò ń fi ayọ̀ kọrin nítorí iṣẹ́ ọwọ́ rẹ.
5 Iṣẹ́ ọwọ́ rẹ tóbi pupọ, OLÚWA!Èrò rẹ sì jinlẹ̀ pupọ!
6 Òpè eniyan kò lè mọ̀,kò sì le yé òmùgọ̀:
7 pé bí eniyan burúkú bá tilẹ̀ rú bíi koríko,tí gbogbo àwọn aṣebi sì ń gbilẹ̀,ó dájú pé ìparun ayérayé ni òpin wọn.
8 Ṣugbọn ẹni àgbéga títí lae ni ọ́, OLUWA.
9 Wò ó, OLUWA, àwọn ọ̀tá rẹ yóo parun;gbogbo àwọn aṣebi yóo sì fọ́n ká.
10 Ṣugbọn o ti gbé mi ga, o ti fún mi lágbára bíi ti ẹfọ̀n;o ti da òróró dáradára sí mi lórí.