7 pé bí eniyan burúkú bá tilẹ̀ rú bíi koríko,tí gbogbo àwọn aṣebi sì ń gbilẹ̀,ó dájú pé ìparun ayérayé ni òpin wọn.
8 Ṣugbọn ẹni àgbéga títí lae ni ọ́, OLUWA.
9 Wò ó, OLUWA, àwọn ọ̀tá rẹ yóo parun;gbogbo àwọn aṣebi yóo sì fọ́n ká.
10 Ṣugbọn o ti gbé mi ga, o ti fún mi lágbára bíi ti ẹfọ̀n;o ti da òróró dáradára sí mi lórí.
11 Mo ti fi ojú mi rí ìṣubú àwọn ọ̀tá mi,mo sì ti fi etí mi gbọ́ ìparun àwọn ẹni ibi tí ó gbé ìjà kò mí.
12 Àwọn olódodo yóo gbilẹ̀ bí igi ọ̀pẹ,wọn óo dàgbà bí igi kedari ti Lẹbanoni.
13 Wọ́n dàbí igi tí a gbìn sí ilé OLUWA,tí ó sì ń dàgbà ninu àgbàlá Ọlọrun wa.