6 Wọ́n ń pa àwọn opó ati àwọn àlejò,wọ́n sì ń pa àwọn aláìníbaba;
7 wọ́n ń sọ pé, “OLUWA kò rí wa;Ọlọrun Jakọbu kò ṣàkíyèsí wa.”
8 Ẹ jẹ́ kí ó ye yín,ẹ̀yin tí ẹ ya òpè jùlọ láàrin àwọn eniyan!Ẹ̀yin òmùgọ̀, nígbà wo ni ẹ óo gbọ́n?
9 Ṣé ẹni tí ó dá etí, ni kò ní gbọ́ràn?Àbí ẹni tí ó dá ojú, ni kò ní ríran?
10 Ṣé ẹni tí ń jẹ àwọn orílẹ̀-èdè níyà,ni kò ní jẹ yín níyà?Àbí ẹni tí ń fún eniyan ní ìmọ̀, ni kò ní ní ìmọ̀?
11 OLUWA mọ èrò ọkàn ọmọ eniyan,ó mọ̀ pé afẹ́fẹ́ lásán ni.
12 Ayọ̀ ń bẹ fún ẹni tí o bá báwí, OLUWA,tí o sì kọ́ ní òfin rẹ,