39 Nígbà tí wọ́n dínkù, tí a rẹ̀ wọ́n sílẹ̀,nípa ìnira, ìpọ́njú, ati ìṣòro,
40 ó da ẹ̀gàn lu àwọn ìjòyè,ó sì mú kí wọn máa rìn kiri ní aṣálẹ̀,níbi tí kò sí ọ̀nà.
41 Ṣugbọn ó yọ aláìní kúrò ninu ìpọ́njú,ó sì mú kí ìdílé wọn pọ̀ sí i bí agbo ẹran.
42 Àwọn olódodo rí i, inú wọn dùn,a sì pa àwọn eniyan burúkú lẹ́nu mọ́.
43 Kí ẹni tí ó gbọ́n kíyèsí nǹkan wọnyi;kí ó sì fi òye gbé ìfẹ́ OLUWA tí kì í yẹ̀.